1 Olúwa, rántí Dafidi
2 Ẹni tí ó ti búra fún Olúwa,
3 Nítòótọ́, èmi kì yóò wọ inú àgọ́ ilé mi lọ,
4 Èmi kì yóò fi oorun fún ojú mi,
5 títí èmi ó fi rí ibi fún Olúwa,
6 Kíyèsi i, àwa gbúròó rẹ̀ ni Efrata:
7 Àwa ó lọ sínú àgọ́ rẹ̀:
8 Olúwa, dìde sí ibi ìsinmi rẹ:
9 Kí a fi òdodo wọ àwọn àlùfáà rẹ:
10 Nítorí tí Dafidi ìránṣẹ́ rẹ̀,
11 Olúwa ti búra nítòótọ́ fún Dafidi,
12 Bí àwọn ọmọ rẹ̀ yóò bá pa májẹ̀mú mi mọ́
13 Nítorí tí Olúwa ti yan Sioni:
14 Èyí ni ibi ìsinmi mi láéláé:
15 Èmi yóò bùkún oúnjẹ rẹ̀ púpọ̀púpọ̀:
16 Èmi yóò sì fi ìgbàlà wọ àwọn àlùfáà rẹ̀:
17 Níbẹ̀ ni èmi yóò gbé mú ìwo Dafidi yọ̀,
18 Àwọn ọ̀tá rẹ̀ ni èmi yóò fi ìtìjú wọ̀: