Números 24

YOR

1 Nísinsin yìí nígbà tí Balaamu rí i wí pé ó tẹ́ Olúwa lọ́rùn láti bùkún àwọn Israẹli, kò lo ọ̀nà ìṣoṣó gẹ́gẹ́ bí ti ìgbà ìṣáájú, ṣùgbọ́n ó yí ojú rẹ̀ sí apá aginjù.

2 Nígbà tí Balaamu wo ìta ó sì rí Israẹli tí wọ́n pàgọ́ gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yà wọn, Ẹ̀mí Ọlọ́run sì bà sórí rẹ̀

3 ó sì sọ àsọtẹ́lẹ̀ rẹ̀,

4 àsọtẹ́lẹ̀ ẹni tí ó gbọ́ ọ̀rọ̀ Ọlọ́run,

5 “Àgọ́ rẹ ti dára tó, ìwọ Jakọbu,

6 “Gẹ́gẹ́ bí àfonífojì tí ó tàn jáde,

7 Omi yóò sàn láti inú garawa:

8 “Ọlọ́run mú wọn jáde láti Ejibiti wá;

9 Ó tẹríba ó sì dùbúlẹ̀ bí kìnnìún,

10 Nígbà náà ni ìbínú Balaki sì dé sí Balaamu. Ó sì fi ọwọ́ lu ọwọ́ ó wí pé, “Mo pè ọ́ láti bú àwọn ọ̀tá mi ṣùgbọ́n o tún bùkún fún wọn nígbà mẹ́ta yìí.

11 Nísinsin yìí sálọ sí ibùjókòó rẹ! Èmi ti rò láti sọ ọ́ di ẹni ńlá, ṣùgbọ́n Olúwa tí fà ọ́ sẹ́yìn láti gba èrè yìí.”

12 Balaamu dá Balaki lóhùn, “Ǹjẹ́ èmi kò sọ fún àwọn ìránṣẹ́ tí o rán sí mi wí pé,

13 ‘Kódà bí Balaki bá fún mi ní ààfin rẹ̀ tí ó kún fún fàdákà àti wúrà, èmi kò le ṣe ohunkóhun lọ́wọ́ ara mi, yálà búburú tàbí rere, láti kọjá òfin Olúwa: ohun tí Olúwa bá wí ni èmi ó sọ’?

14 Nísinsin yìí mò ń padà lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn mi, ṣùgbọ́n jẹ́ kí èmi kí ó kìlọ̀ fún ọ nítorí nǹkan tí àwọn ènìyàn wọ̀nyí yóò ṣe sí àwọn ènìyàn rẹ ní ọjọ́ iwájú.”

15 Nígbà náà ni ó bẹ̀rẹ̀ òwe:

16 ẹni tó gbọ́ ọ̀rọ̀ Ọlọ́run ń wí,

17 “Mo rí i, ṣùgbọ́n kì í ṣe ìsinsin yìí.

18 Wọn yóò borí Edomu;

19 Olórí yóò jáde láti Jakọbu

20 Nígbà náà ni Balaamu rí Amaleki ó sì bẹ̀rẹ̀ òwe:

21 Nígbà náà ní ó rí ará Keni ó sì bẹ̀rẹ̀ òwe:

22 síbẹ̀ ẹ̀yin ará Keni ni yóò di píparun

23 Nígbà náà ni ó bẹ̀rẹ̀ òwe rẹ̀:

24 Ọkọ̀ yóò wá láti ibùdókọ̀ Kittimu;

25 Nígbà náà ni Balaamu dìde ó sì padà sí ilé rẹ̀, Balaki sì lọ ní ọ̀nà tirẹ̀.

Ler em outra tradução

Comparar lado a lado