Jeremias 12

YOR

1 Olúwa, olódodo ni ọ́ nígbàkígbà,

2 Ó ti gbìn wọ́n, wọ́n sì ti fi egbò múlẹ̀,

3 Síbẹ̀ o mọ̀ mí ní Olúwa,

4 Yóò ti pẹ́ tó tí ọ̀gbẹlẹ̀ yóò fi wà,

5 Bí ìwọ bá ń bá ẹlẹ́ṣẹ̀ sáré,

6 Àwọn arákùnrin rẹ àti àwọn

7 Èmi yóò kọ ilé mi sílẹ̀,

8 Ogún mi ti rí sí mi

9 Ogún mi kò ha ti rí sí mi

10 Ọ̀pọ̀lọpọ̀ olùṣọ́-àgùntàn ni yóò sì ba ọgbà àjàrà mi jẹ́,

11 A ó sọ ọ́ di aṣálẹ̀ ilẹ̀

12 Gbogbo ibi gíga tí ó wà nínú aṣálẹ̀

13 Àlìkámà ni wọn yóò gbìn, ṣùgbọ́n ẹ̀gún ni wọn yóò ká,

14 Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Ní ti gbogbo àwọn aládùúgbò mi búburú tí wọ́n gbẹ́sẹ̀ lé ogún tí mo fún àwọn ènìyàn Israẹli mi, Èmi yóò fà wọ́n tu kúrò lórí ilẹ̀ wọn, èmi yóò fa ìdílé Juda tu kúrò ní àárín wọn.

15 Ṣùgbọ́n tí mo bá fà wọ́n tu tán, Èmi yóò padà yọ́nú sí wọn. Èmi yóò sì padà fún oníkálùkù ní ogún ìní rẹ̀ pẹ̀lú ilẹ̀ ìní oníkálùkù.

16 Bí wọ́n bá sì kọ ìwà àwọn ènìyàn mi, tí wọ́n sì fi orúkọ mi búra wí pé, ‘Níwọ̀n bí Olúwa ń bẹ láààyè,’ gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti kọ́ àwọn ènìyàn mi láti fi Baali búra, nígbà náà ni a ó gbé wọn ró láàrín àwọn ènìyàn mi.

17 Ṣùgbọ́n bí orílẹ̀-èdè kan kò bá gbọ́, Èmi yóò fà á tu pátápátá, èmi yóò sì pa wọ́n run,” ni Olúwa wí.

Ler em outra tradução

Comparar lado a lado