1 “Àyà sì fò mi sí èyí pẹ̀lú,
2 Fetísílẹ̀! Fetísílẹ̀, kí ẹ sì gbọ́ ìró ohùn rẹ̀,
3 Ó ṣe ìlànà rẹ̀ ní ìsàlẹ̀ ọ̀run gbogbo,
4 Lẹ́yìn mọ̀nàmọ́ná ohùn kan fọ̀ ramúramù;
5 Ọlọ́run fi ohùn rẹ̀ sán àrá ní ọ̀nà ìyanu;
6 Nítorí tí ó wí fún yìnyín pé, ‘Ìwọ rọ̀ sílẹ̀ ayé,’
7 Ó fi èdìdì di ọwọ́ gbogbo ènìyàn kí gbogbo wọn kí ó lè mọ iṣẹ́ rẹ̀,
8 Nígbà náà ní àwọn ẹranko wọ inú ihò lọ,
9 Láti ìhà gúúsù ni ìjì àjàyíká tí jáde wá,
10 Nípa ẹ̀mí Ọlọ́run a fi ìdí omi fún ni,
11 Pẹ̀lúpẹ̀lú ó fi omi púpọ̀ mú àwọsánmọ̀ wúwo,
12 Àwọn wọ̀nyí yí káàkiri nípa ìlànà rẹ̀,
13 Ó mú àwọsánmọ̀ wá, ìbá ṣe fún ìkìlọ̀,
14 “Jobu, dẹtí sílẹ̀ sí èyí;
15 Ṣe ìwọ mọ àkókò ìgbà tí Ọlọ́run ṣe wọ́n lọ́jọ̀,
16 Ṣé ìwọ mọ ìgbà tí àwọsánmọ̀ í fò lọ,
17 Ìwọ ẹni ti aṣọ rẹ̀ ti máa n gbóná,
18 Ìwọ ha ba tẹ́ pẹpẹ ojú ọ̀run, tí ó dúró ṣinṣin,
19 “Kọ́ wa ní èyí tí a lè wí fún un;
20 A ó ha wí fún un pé, èmi fẹ́ sọ̀rọ̀?
21 Síbẹ̀ nísinsin yìí ènìyàn kò rí
22 Wúrà dídán ti inú ìhà àríwá jáde wá;
23 Nípa ti Olódùmarè àwa kò le wádìí rẹ̀, ó rékọjá ní ipá;
24 Nítorí náà ènìyàn ha máa bẹ̀rù rẹ̀,