1 Ìgbà náà ní Jobu dáhùn, ó sì wí pé,
2 “Èmi ti gbọ́ irú ohun púpọ̀ bẹ́ẹ̀ rí
3 Ọ̀rọ̀ asán lè ni òpin?
4 Èmi pẹ̀lú le sọ bí ẹ̀yin;
5 Èmi ìbá fi ọ̀rọ̀ ẹnu mi gbà yín ni ìyànjú,
6 “Bí èmi tilẹ̀ sọ̀rọ̀, ìbìnújẹ́ mi kò lọ;
7 Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, ó dá mi lágara;
8 Ìwọ fi ìhunjọ kùn mí lára, èyí tí o jẹ́rìí tì mí;
9 Ọlọ́run fi i ìbínú rẹ̀ fà mí ya, ó sì gbóguntì mí;
10 Wọ́n ti fi ẹnu wọn yẹ̀yẹ́ mi;
11 Ọlọ́run ti fi mí lé ọwọ́ ẹni búburú,
12 Mo ti jókòó jẹ́ẹ́, ṣùgbọ́n ó fà mí já;
13 àwọn tafàtafà rẹ̀ dúró yí mi káàkiri.
14 Ìbàjẹ́ lórí ìbàjẹ́ ní ó fi bà mí jẹ́;
15 “Mo rán aṣọ ọ̀fọ̀ bò ara mi,
16 Ojú mi ti pọ́n fún ẹkún,
17 Kì í ṣe nítorí àìṣòótọ́ kan ní ọwọ́ mi;
18 “Háà! Ilẹ̀ ayé, ìwọ má ṣe bò ẹ̀jẹ̀ mi,
19 Ǹjẹ́ nísinsin yìí kíyèsi i, ẹlẹ́rìí mi ń bẹ ní ọ̀run,
20 Àwọn ọ̀rẹ́ mi ń fi mí ṣẹ̀sín,
21 ìbá ṣe pé ẹnìkan le è máa ṣe alágbàwí fún ẹnìkejì lọ́dọ̀ Ọlọ́run,
22 “Nítorí nígbà tí iye ọdún díẹ̀ rékọjá tán,