1 Nígbà náà ni Jakọbu ránṣẹ́ pe àwọn ọmọ rẹ̀, ó sì wí pé, “Ẹ kó ara yín jọ pọ̀, kí n le è sọ ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ ní ọjọ́ iwájú fún un yín.
2 “Ẹ kó ara yín jọ pọ̀, kí ẹ sì tẹ́tí, ẹ̀yin ọmọ Jakọbu;
3 “Reubeni, ìwọ ni àkọ́bí mi,
4 Ẹni ríru bí omi Òkun, ìwọ kì yóò tayọ mọ́,
5 “Simeoni àti Lefi jẹ́ arákùnrin—
6 Kí ọkàn mi má ṣe ni àṣepọ̀ pẹ̀lú wọn,
7 Ìfibú ni ìbínú wọn nítorí tí ó gbóná púpọ̀,
8 “Juda, àwọn arákùnrin rẹ yóò yìn ọ,
9 Ọmọ kìnnìún ni ọ́, ìwọ Juda,
10 Ọ̀pá oyè kì yóò kúrò ní Juda
11 Yóò má so ọmọ ẹṣin rẹ̀ mọ́ igi àjàrà,
12 Ojú rẹ̀ yóò rẹ̀ dòdò ju wáìnì lọ,
13 “Sebuluni yóò máa gbé ní etí Òkun,
14 “Isakari jẹ́ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ alágbára
15 Nígbà tí ó bá rí bí ibi ìsinmi òun ti dára tó,
16 “Dani yóò ṣe ìdájọ́ àwọn ènìyàn rẹ̀
17 Dani yóò jẹ́ ejò ni pópónà
18 “Mo ń dúró de ìtúsílẹ̀ rẹ, Olúwa.
19 “Ẹgbẹ́ ogun àwọn ẹlẹ́ṣin yóò kọlu Gadi,
20 “Oúnjẹ Aṣeri yóò dára;
21 “Naftali yóò jẹ́ abo àgbọ̀nrín
22 “Josẹfu jẹ́ àjàrà eléso,
23 Pẹ̀lú ìkorò, àwọn tafàtafà dojú ìjà kọ ọ́,
24 Ṣùgbọ́n ọrun rẹ̀ dúró ni agbára,
25 nítorí Ọlọ́run baba rẹ tí ó ràn ọ́ lọ́wọ́,
26 Ìbùkún baba rẹ pọ̀ púpọ̀
27 “Benjamini jẹ́ ìkookò tí ó burú;
28 Gbogbo ìwọ̀nyí ni àwọn ẹ̀yà Israẹli méjìlá, èyí sì ni ohun tí baba wọn sọ fún wọn nígbà tí ó súre fún wọn, tí ó sì fún ẹnìkọ̀ọ̀kan ní ìbùkún tí ó tọ́ sí i.
29 Nígbà náà ni ó fún wọn ní àwọn ìlànà yìí, “Ọjọ́ ikú mi kù fẹ́ẹ́rẹ́. Kí ẹ sin mí sí ibojì pẹ̀lú àwọn baba mi ní inú àpáta ní ilẹ̀ Hiti ará Efroni.
30 Ihò àpáta tí ó wà ní ilẹ̀ Makpela, nítòsí Mamre ní Kenaani, èyí tí Abrahamu rà gẹ́gẹ́ bí ilẹ̀ ìsìnkú lọ́wọ́ Efroni ará Hiti pẹ̀lú ilẹ̀ rẹ̀.
31 Níbẹ̀ ni a sin Abrahamu àti aya rẹ̀ Sara sí, níbẹ̀ ni a sin Isaaki àti Rebeka aya rẹ̀ sí, níbẹ̀ sì ni mo sìnkú Lea sí.
32 Ilẹ̀ náà àti ihò àpáta tí ó wà nínú rẹ̀ ni a rà lọ́wọ́ ará Hiti.”
33 Nígbà tí Jakọbu ti pàṣẹ yìí fún àwọn ọmọ rẹ̀, ó gbé ẹsẹ̀ rẹ̀ sókè sórí ibùsùn, ó sì kú, a sì ko jọ pọ̀ mọ́ àwọn ènìyàn rẹ̀.