Êxodo 15

YOR

1 Nígbà náà ni Mose àti àwọn ọmọ Israẹli kọ orin yìí sí Olúwa,

2 Olúwa ni agbára àti orin mi;

3 Ológun ni Olúwa,

4 kẹ̀kẹ́ ogun Farao àti ogun rẹ̀

5 Ibú omi bò wọ́n mọ́lẹ̀;

6 “Ọwọ́ ọ̀tún rẹ, Olúwa,

7 “Nínú agbára ńlá rẹ ti ó tóbi

8 Pẹ̀lú èémí imú rẹ ni

9 Ọ̀tá ń gbéraga, ó ń wí pé,

10 Ìwọ fẹ́ èémí rẹ,

11 Ta ni nínú àwọn òrìṣà

12 “Ìwọ na apá ọ̀tún rẹ,

13 Nínú ìfẹ́ rẹ ti kì í sákí Ìwọ ṣe amọ̀nà

14 Orílẹ̀-èdè yóò gbọ́ wọn yóò wárìrì.

15 Ìbẹ̀rù yóò mú àwọn ìjòyè Edomu,

16 Ìbẹ̀rù bojo yóò ṣubú lù wọ́n, nítorí

17 Ìwọ yóò mú wọn wá láti gbìn wọ́n

18 “Olúwa yóò jẹ ọba

19 Nígbà ti ẹṣin Farao, kẹ̀kẹ́ ogun àti àwọn ẹlẹ́ṣin rẹ̀ wọ inú Òkun, Olúwa mú kí omi òkun padà bò wọ́n mọ́lẹ̀, ṣùgbọ́n àwọn ọmọ Israẹli rìn lórí ìyàngbẹ ilẹ̀ la òkun kọjá.

20 Miriamu wòlíì obìnrin, arábìnrin Aaroni, mú ohun èlò orin ni ọwọ́ rẹ̀, gbogbo àwọn obìnrin sì jáde tẹ̀lé e pẹ̀lú ìlù òun ijó.

21 Miriamu kọrin sí wọn báyìí pé,

22 Nígbà náà ni Mose ṣe amọ̀nà àwọn ènìyàn Israẹli jáde láti Òkun Pupa lọ sínú ijù Ṣuri. Wọ́n lọ ní ìrìn ọjọ́ mẹ́ta sínú ijù náà, wọn kò sì rí omi.

23 Nígbà tí wọ́n dé Mara, wọn kò lè mu omi Mara nítorí omi náà korò. (Nítorí náà ni a ṣe pe ibẹ̀ ni Mara: ibi ìkorò.)

24 Àwọn ènìyàn ń kùn sí Mose wí pé, “Kí ni àwa yóò mu?”

25 Mose sì ké pe Olúwa, Olúwa sì fi igi kan hàn án, ó sì sọ igi náà sínú omi, omi náà sì dùn.

26 Ó wí pé, “Bí ìwọ bá fetísílẹ̀ dáradára sí òfin Olúwa Ọlọ́run, ti ìwọ sì ṣe ohun tí ó tọ́ ni ojú rẹ̀, ti ìwọ sì tẹ̀lé ohun tí ó pàṣẹ, ti ìwọ si pa ìlànà rẹ̀ mọ́. Èmi kì yóò jẹ́ kí èyíkéyìí nínú àwọn ààrùn wọ̀n-ọn-nì ti mo mú wá sórí àwọn ará Ejibiti wá sí ara rẹ, nítorí Èmi ni Olúwa ti ó mú ọ láradá.”

27 Nígbà ti wọ́n dé Elimu, níbi ti kànga omi méjìlá àti àádọ́rin ọ̀pẹ gbé wà, wọ́n pàgọ́ síbẹ̀ ni etí omi.

Ler em outra tradução

Comparar lado a lado