1 Mo ti dé inú ọgbà mi, arábìnrin mi, ìyàwó mi;
2 Mo ti sùn ṣùgbọ́n ọkàn mi jí.
3 Mo ti bọ́ aṣọ ìgúnwà mi
4 Olùfẹ́ mi na ọwọ́ rẹ̀ láti inú ihò ìlẹ̀kùn
5 Èmi dìde láti ṣílẹ̀kùn fún olùfẹ́ mi,
6 Èmi ṣí ìlẹ̀kùn fún olùfẹ́ mi,
7 Àwọn olùṣọ́ tí ń ṣọ́ ìlú rí mi
8 Ẹ̀yin ọmọbìnrin Jerusalẹmu, mo bẹ̀ yín
9 Kí ni olùfẹ́ rẹ fi dára ju àwọn tókù lọ,
10 Olùfẹ́ mi ní ìtànṣán ó sì pọ́n
11 Orí rẹ̀ rí bí i wúrà tí ó dára jùlọ
12 Ojú rẹ̀ rí bí i ti àdàbà
13 Ẹ̀rẹ̀kẹ́ rẹ̀ rí bí ibùsùn tùràrí
14 Apá rẹ̀ rí bí i ọ̀pá wúrà,
15 Ẹsẹ̀ rẹ̀ rí bí i òpó mabu
16 Ẹnu rẹ̀ jẹ́ adùn fún ara rẹ̀